Orólẹ̀èdè wa Nàijírìa, ilẹ̀ olóminira Niger àti orílẹ̀èdè Chad ti ńsisẹ́ lórí àkànse ètò láti fi se àtúnse ibùdó adágún odò Chad, kí ètò ìgbáyégbádùn ba lè wà fáwọn èèyàn tó wà lágbègbè adágún odò na.

Ọga àgbà àjọ kan tí wọ́n ń pè ní National Agency for the great green wall, ọ̀mọ̀wé Bukar Hassan ló sọ̀rọ̀ yí lẹ́yìn ìpàdé kan tí wọ́n se lórí bí ilẹ̀ se ọgbẹlẹ̀, nílu New Delhi lórílẹ̀èdè India.

Ọmọwe Hassan sọ pé, níwọ̀n ìgbà tó jẹ́ pé kò sí orílẹ̀èdè tọ́rọ̀ ọ̀rọ̀ àyíká ko kan, àjọsepọ̀ láàrin àwọn orílẹ̀èdè mẹ́tẹ̀ẹ̀ta yo jẹ kí wọn lè sàtúnse sọ́rọ̀ isk àgbẹ̀ lágbayé na, bákannà ni àwọn ilẹ̀ tó ti sáà, yo di ọlọ́ra padà, tí gbe ayé yo sì túbọ̀ rọrùn fáwọn èèyàn tó wà nítòsí adágún odò Chad na.

Kemi Ogunkóla/Lara Ayọade

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *