Àjọ olùlanilọ́yẹ̀ aráálu sojúse ẹni, NOA, ti sàlàyé ìdí tó fi sepàtàkì kájọsepọ̀ tó dán mọ́ràn wà láarin àwọn ọmọ orílẹ̀dè yíì láifi tẹ̀sìn, tẹ̀yà tàbí èyíkèyí ẹgbẹ́ òsèlú kankan se, fálafìa orílẹ̀dè yíì.

Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ níbi ètò ìlanilọ́yẹ̀ kan tó wáyé nílu Ìbàdàn èyí tó ń sàmì àyájọ́ àláfìa fún tọdún yíì, olùdarí àjọ NOA, nípinlẹ̀ Ọyọ, arábìnrin Dọlapọ Dosunmu tọ́kasi pé, kò sèyí kèmí orílẹ̀dè tó lè ni ìdàgbàsókè láarin àyíká tí rúkè-rúdò ti ń wáyé.

Arábìnrin Dosunmu sàlàyé pé, àjọ náà yóò tẹ̀síwájú lórí bálafìa se sepàtàkì sí ìgbáyégbádùn  ètò ọrọ̀ ajé orílẹ̀dè títí dìgbà tálafìa yóò fi degun àtẹran ara ilẹ̀ Nàijírìa.

Kẹmi Ogunkọla/Famakin Rotimi

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *