Iléésẹ́ asọ́bodè nílẹ̀ yíì, ti kéde fífòfinde láinigbèdéke lórí kíkó ọjà wọlé tàbì fífi ọjà sọwọ́ sílẹ̀ òkèrè láti ẹnu bodè ilẹ̀ yíì.

Ọga-àgbà fúnleesẹ́ as abodè, Ọ̀gágun Fẹ̀yìntì Hameed Ali, ẹni tó sọ̀rọ̀ yíì níbi ìpàdé àwọn oníròyìn tówáyé nílu Abuja, sọpé ilé olómìnìra Niger náà ti fòfinde kíkó ìrẹsì wọlé láti ilẹ̀ náà sórílẹ̀èdè Nàijírìa nítorí ẹnubodè ilẹ̀ yíì tóti di títìpa.

Èyí tún níìse pẹ̀lú bí àjọ tó ńrísí ìwọlé jáde nílẹ̀ yíì, se fìdirẹ̀ múlẹ̀ pe, òhun ti dáà èyàn tootoo ẹgbẹ̀rúnkanlélọ́gọ́fà dúró láti wọ ilẹ̀ Nàijírìa láti ogúnjọ́ osù kẹjọ ọdún yíì, nígbàtí ẹnu bodè ilẹ̀ yíì kòtíjẹ títìpa sansan.

Kẹmi Ogunkọla/Ọmọlọla Alamu

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *