Àarẹ Muhammadu Buhari ti sèkìlọ̀ fáwọn èèyàn láti dẹ́kun a ńfọwọ́kan àwọn wáyà iná ọba káákiri ile yíì.

Nínú àtẹ̀jáde tí àarẹ Buhari kọ látipasẹ̀ olùbádámọ̀ràn rẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ ìròyìn àti ìba aráálu sọ̀rọ̀, Fẹmi Adesina, àarẹ kẹ́dùn pẹ̀lú àwọn tó faragbá nínú ìsẹ̀lẹ̀ jàmbá iná tó wáyé lọ́jọ́bọ̀ ní Ìjegun ńpinlẹ̀ Èkó.

Àarẹ Buhari wá késí àwọn elétò àabò láti ri pé àwọn táje ìwà ìbàjẹ́ yi símọ́ lórí fojú winá òfin ó sì gbàdúrà fáwọn tó pàdánù ẹ̀mí wọn pé kí Ọlọrun tẹ́ wọn sáfẹ́fẹ́ rere kí Ọlọrun sì tu mọ̀lẹ́bí wọn nínú.

Kẹmi Ogunkọla/Modupe Tọba

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *