Ilé asòfin ìpínlẹ̀ Ọyọ ti fọwọ́sí àwọn àbá òfin kan láti sèdásílẹ̀ ilé-isẹ́ ọ̀rọ̀ agbára, ilé-isẹ́ olókoowò àti tídasẹ́ ajé sílẹ̀, ilé-isẹ́ tón rí sọ́rọ̀ isẹ́ òde, ohun amáyédẹrùn àti tètòrìnà, tófomọ́ ilé-isẹ́ tó ń rí sọ́rọ̀ àwọn obìnrin.

Àbá òfin náà tíwọ́n fọwọ́ sí níbi ìjóko ilé tó wáyé níbamu pẹ̀lú ìpinu Gómìnà Seyi Makinde láti mátunse tó yẹ báwọn ilé-isẹ́ náà.

Nígbà tón sọ̀rọ̀ lórí ìdásílẹ̀ ilé-isẹ́ ọrọ̀ agbára, asòfin tó ńsojú ẹkùn ìdìbò Kájọlà, ọ̀gbẹ́ni Mustapha Akeem, tọ́kasi pé, èróngbà ilé-isẹ́ náà ni láti fikún agbára iná ọba táwọn olùgbé nílò nípinlẹ̀ yíì.

Gẹ́gẹ́ bó se wípé, àwọn ojúse ilé-isẹ́ náà ni kò mágbega àti ìdàgbàsókè báwọn ìlànà àtẹẹle nídi ọ̀rọ̀ ohun àmúsagbára látiri dájú pé, iná ọba dúró réè fógunlọ́gọ̀ àwọn olùgbé tón bẹ nípinlẹ̀ Ọyọ àti láti sọ́ọ́di ibùdó ìdókoowò tó lóorin.

Nínú ọ̀rọ̀ tiẹ, ọ̀gbẹ́ni Adebọ Ogundoyin fọwọ́ ìdánilógú sọ̀yà pe, ilé asòfin òhun ti se àgbéyẹ̀wò tó gbópọn lórí àwọn àbá òfin kó tó dipé ójẹ́ bíbuwọ́lù, kó lè ba sisẹ́ tíwọ́n torírẹ̀ gbekalẹ̀.

Wojuade

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *