Lóòrọ̀ òní, àwọn òsìsẹ́ ọba ni kò rọrùn fún láti wọ ilésẹ́ ìjọba ní Secretariat, Agodi ìbàdàn, lẹ́yìn tí àwọn tó ní ìpèníjà ara ńfẹ̀húnúhàn lórí ẹ̀sùn pé ìjọba dẹ́yẹ sí wọn.

Akọ̀ròyìn ilésẹ́ Radio Nigeria jábọ̀ pé àwọn àkàndá ẹ̀dá yi ni wọ́n ńgbé oníruru àkọlé lọ́wọ́ láti fi ẹ̀húnúhàn wọn hàn.

Àwọn tón fẹ̀húnúhàn yi, fẹ̀sùn kan ìjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ pé, wọ́n kò fi àwọn sínú àwọn tí wọ́n gbà sísẹ́ láipẹ yi, tí àjọ tón mójútó ọ̀rọ̀ àwọn olùkọ́ nípinlẹ̀ ọ̀yọ́ se agbátẹrù.

Akọ̀ròyìn jábọ̀ pé àwọn ẹ̀sọ́ alábo wànkẹlẹ láti fẹsẹ̀ òfin múlẹ̀.

Ayọade/Afonja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *