Gómìonà Seyi Makinde tìpínlẹ̀ ọ̀yọ́, ti se ìfilọ́lẹ̀ ìsí àkọ̀kọ̀, sísètò ìjọba lórí òpó ẹ̀rọ ayélujára pẹ̀lú ẹ̀rọ ayábiasa tó lé ní ẹgbẹ̀rún kan níye, tí àwọn ilésẹ́ ìjọba àti ẹ̀ka yo ma lo nípinlẹ̀ yí.

Ètò ọ̀hún lówáyé níbùdó ìmọ̀ ẹ̀rọ ayélujára tó wà ní secretariat Agodi ìbàdàn.

Gómìnà Makinde lásìkò tón wo àwọn ẹ̀rọ ayárabíasa tí wọ́n sẹ̀sẹ̀ rà yí, se lálàyé pé, àfojúsùn ìsèjọba òun ni láti gbé ètò ìjọba lé orí ẹ̀rọ ayálujára, kó kúrò ní bí wọ́n tin se látẹ̀yìnwá.

Nígbà tón mú Gómìnà àti ikọ̀ tó kọ́wọrìn pẹ̀lú rẹ̀, yípo àwọn on èlò yí, olùdámọ̀ràn pàtàkì sí Gómìnà lórí ọ̀rọ̀ ìròyìn àti àbáraẹni sọ̀rọ̀ lójú òpó ayélujára, ọ̀gbẹ́ni Bayọ Akande fọwọ́ ìdánilójú sọ̀yà pé, ilésẹ́ náà ti setán fún sísàmúlò ìsèjọba nílànà ìgbàlódé.

AdebisiAfọnja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *