Àwọn tón sisẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ni wọn ti gbà níyànjú láti ma fojú ọmọ̀nìyàn wo ìròyìn àwọn tí wọ́n bá lọ láti ìlú kan sí èkejì, láti jẹ́ káwọn arálu nífẹsí gbígbọ́ rẹ̀.
Ọjọgbọn nípa ìmọ̀ isẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ ní ilé ẹ̀kọ́ gíga Nnamdi Azikwe nípinlẹ̀ Anambra, ọ̀jọ̀gbọ́n Ifoma Donu ló sọ̀rọ̀ yí nílu Abuja, lásìkò tón gbé àbọ̀ ìwádi lórí ìròyìn àwọn òsìsẹ́ tón rísí ọ̀rọ̀ àwọn àtìpó, tón pada bọ nílẹ̀ Nàijírìa níbamu pẹ̀lú dídènà àrùn covi.
Ọjọgbọn Donu sọ pé yio dára ìròyìn àwọn tón rin rin àjò , bá jáde lanà tí àwọn arálu àtàwọn tón sofin yo fi le gbọ.
Ó wá gba àwọn akọ̀ròyìn níyànjú láti ma tọ́ọ̀ ìròyìn náà lẹ́yìn, títí tí yo fi ní ìyanjú.
Àwọn alámojútó isẹ́ àkànse nílẹ̀yí, ọ̀gbẹ́ni Austin Erano, sàlàyé pé, ètò náà ni ó wá ńlẹ̀, láti mọ nípàtó ibi tí ìtàntálẹ̀ àrùn covid 19 dé dúró lọ́dọ̀ àwọn òsìsẹ́ àwọn tóń tọ́jú wọn.
Alamu/Afọnja