News Yoruba

Olósèlú Tó Jẹ́ Ọmọbíbí Ilẹ̀ Bàdàn Sọ Pé Ìlànà Àtúntò Ìsèjọba Àpapọ̀ Yo Wójùtú Sí Ìpèníjà Tón Kojú Ilẹ̀ Nàijírìa

Ìlànà àtúntò ètò ìsèjọba àpapọ̀, ni ọ̀nà kan gbóògi láti fi wá ojútu sí ìpèníjà tón kojú ill Nàijírìa.

Ọrọ yí ló tẹnuma olósèlú tó jẹ́ ọmọbíbí ilẹ̀ bàdàn, ọ̀mọ̀wé Fọla Akinọsun jáde nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò pẹ̀lú akọ̀ròyìn ilésẹ́ Radio Nigeria.

Ọmọwe Akinọsun sọ ìdí pàtàkì tó fi yẹ kí ìlànà àtúntò ọ̀tun kó wáyé, láti mádinkù dé bá bí ìjọba àpapọ̀, sén dásí àwọn ǹkan àlùmọ́nì tó jẹ́ ti ìpínlẹ̀ àti ti ẹkun kọ̀kan.

Gẹ́ge bótiwi, gbígbé ìjọba kalẹ̀ fún ìjọb amiran nìkan, kọ lo le wójùtú sí ìpèníjà tó ń bá orílẹ̀ èdè yí fínra, ìdí nìyi tó fi yẹ káwọn tón bèrè fún àtúntò ma ronu lórí ètò ìsèjọba àwarawa nítotọ́.

Lórí ètò àbò, ọ̀mọ̀wé Akinọsun, sọ pé sísàmúlò ìlànà isẹ́ ọlọ́pa nípinlẹ̀ ni yo wójùtú sí ìpèníjà ètò àbò.

Banjọ/Afọnja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *