Àjọ ẹ̀sọ́ ojú pópó nílẹ̀ Náigírìa ti sọpé dandan ni fífi sára ọkọ̀ ohun sísàmúlò ẹ̀rọ asòdinwọ̀n eré sísá fáwọn awakọ̀ kólè mú àdínkùn bá eré àsápajúdé lójú pópó.

Ọga àgbà àjọ náà fún ìpínlẹ̀ Ògùn, ọ̀gbẹ́ni Ahmed umar ló yọjú ọ̀rọ̀ náà síta lásìkò ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú àwọn akọ̀ròyìn nílu Ọta.

Ọgbẹni Umar wá rọ àwọn onímọ̀ tó láti ri dájú pé wọ́n sọ ẹrọ ohun gẹ́gẹ́bí ǹkan tó se kókó kólè mú àdínkù bá eré sísá.

Ó sàlàyé pé àjọ FRSC, ti mú ọrọ náà lọ́kunkúndùn kítẹ̀síwájú le máà ba .

Bákanà náà lótún sọ pàtàkì ẹ̀rọ ọhun fáwọn ọkọ̀ ẹrun ńla ńla, àtàwọn awàkọ̀ bọ́sí ero.

Ọgbẹni Umar wá rọ àwọn awakọ̀ láti lọ sórí ikanni orí ẹ̀rọ ayélujára àjọ náà láti darapọ̀ mọ́ alámojútó ereọ ohun láwọn ìpínlẹ̀ nítorípé ìpínlẹ̀ kọ́ọ̀kan lóni alámojútó lọtọọtọ.

Ayọade/Ọlaọpa

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *