News Yoruba

Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkìtì ti pa ní dandan fún àwọn òsìsẹ́ lẹ́ka tó se kókó nípinlẹ̀ náà, láti lọ fún àyẹ̀wò ìlera wọn.

Olórí òsìsẹ́ lọ́fìsì Gómìnà, ọ̀gbẹ́ni Biọdun Ọmọlẹyẹ ló jẹ́ kọ́rọ̀ yi di mímọ̀ nílu Adó Èkìtì, pẹ̀lú àlàyé pé ètò ìgbáyé gbádùn àwọn òsìsẹ́ ló jẹ ìsèjọba tó wà lóde lógún.

Ó wá sọ̀rọ̀ fi dá àwọn òsìsẹ́ lójú pé gbogbo owó èyì tí wọ́n lẹ́tọ sí ni yo jẹ́ sísan, kó tó di wípé ọdún yi yo parí.

 Ọgbẹni Ọmọlẹyẹ wá gba àwọn òsìsẹ́ níyànjú pé, ẹnikẹ́ni tí ìlera rẹ̀ kò bá gbé-isẹ́ èyí tón se, ni kó sọ, kó má ba pa isẹ́ ìjọba lára.

Okareh/Afọnja