Yoruba

Ijoba Ipinle Ekiti ti sun ofin kon le o gbele oni wakati meranlelogun to bere lele lojo isegun nipinle naa sinawju si.

 Akowe iroyin fun Gomina, Ogbeni Yinka Oyebode lo kede oro yi ninnu atejade to fi sita nilu Ado-Ekiti pelu alaye wipe ofin kon le o gbele naa lo sin tesiwaju di ojo miin ojoo re.

 O fi emi ope han si gbogbo eeyan ilu naa fun ifowosowopo won, pelu fifowo soya pe alaafia yoo joba pada nipinle naa laipe ojo.

 Babatunde

Yoruba

Igbimo Alase Ijoba Ipinle Ekiti ti fowosi iyansipo Omooba Ajakaye Adeola Adeniyi gege bi Oluyin ti Iyin Ekiti nijoba ibile  Irepodun/Ifelodun nipinle naa.

Igbese iyansipo naa niwon fowosi nibi ipade pataki igbimo Alase ofun, eleketadinlogun ire re, eyi ti Gomina Kayode Fayemi lewaju fun.  Alakoso feto Iroyin atilaniloye araaly, nipinle naa, Ogbeni Akin Omole lo fidi eyi mule nibi atejade kan tiwon fisita nilu Ado-Ekiti.

Gege balakoso naa sewipe, Omooba Ajakaye Adeniyi lawon Afobaje yan laarin awon eeyan mejo ti oketagidigidi fakale loun ti ni onka ibo to po julo, nini ipade awon Afobaje.  Latogunjo osu kasan odun 2019 nipo Oba Oluyin ti Iyin Ekiti ti sofo, nitori ipapoda Oba John Ademola Ajakaye

Folakemi Wojuade