News Yoruba

Ilé ìgbìmọ̀ asòfin kejì ti ńgbé ìgbésẹ̀ láti fòfinde kíkó àwọn ohun ìjagun wọ orílẹ̀dè yíì.

Àbá òfin ọ̀hún tó wọ́n ti kà fún igbákejì niwọ̀n ti fi sọwọ́ sí ìgbìmọ̀ tí tẹkótó ilé fọ̀rọ̀ ìlànà àti àfẹnukò láti gbéyẹ̀wò.

Ìgbìmọ̀ tẹkótó ilé fọrọ ìlànà àtafẹnukò náà sèpàdé èyítí ọ̀mọ̀wé Nicholas Ossai darí rẹ̀ pẹ̀lú àwọn tọ́tọkàn lórí ọ̀rọ̀ ọ̀hún.

Nínú ọ̀rọ̀ ìkíni kábọ rẹ̀, alága ìgbpimọ̀  shún ọ̀mọ̀wé Ossai, sọ di mímọ̀ pé, ìgbìmọ̀ náà, ti gbé èróngbà òfin tó fẹnukò lélórí kalẹ̀ síwájú pẹ̀lú àkòrí àpérò àjọ ECOWAS, lórí ohun ìjagun.

Ọmọwe Ossai, fikun pé, ìpàdé ọ̀hún wáyé láti lọ jomitoro ọ̀rọ̀ lórí ìgbésẹ̀ àwọn asòfin láti se àgbékalẹ̀ òfin lórí ohun ìjagun.

Alamu/Idogbe

Yoruba

Adarí ilé ìgbìmọ̀ asòfin kejì, ọ̀gbéni Fẹmi Gbajabiamila ti pè fún ìpàdé kan, lórí ọ̀nà láti wójùtú sọ́rọ̀ àwọn tó ń wáyé láàrin àwọn darandaran àtàwọn agbègbè tón gbawọn lálejò lápá àríwá orílẹ̀èdè yíì, kó tó di pé ọ̀rọ̀ burú kọjá bó se yẹ.

Ìlú Abuja lọ̀gbéni Gbajabiamila ti sọ̀rọ̀ yíì di mímọ̀ pẹ̀lú àlàyé pé, ẹkùn ìwọ̀ óòrùn gúsù ko gbodọ di gbogbo ọ̀rọ̀ ru apá àríwá, bẹ́ẹ̀ náà si ni, àríwá ko gbọdọ eya lo gbọdọ máà bọ́wọ́ fún rawọn nípasẹ̀ okòòwò, itan tófimọ́ àsà kóówá.

Kò sài tọ́kasi pé, ọ̀rọ̀ tóníse pẹ̀lú ìwà ọ̀daràn, páàpajùlọ ìwà ìpànìyàn gbọdọ lọ sópin ìgbàgbé.

Ọgbẹni Gbajabiamila tó gbóríyìn fún ìyànsípò àwọn ọ̀gá aláàbo tuntun látọ̀dọ̀ àarẹ Buhari sàpèjúwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí èyí tó se àtẹ́wọ́gbà kò sài fikun pé, ilé ìgbìmọ̀ àpapọ̀ setán láti pèsè ààyè ìrọ̀rùn fún wọn láti fi sisẹ́ wọn dójú àmì.

Blessing/Wojuade