Láti osù tónbọ̀ lọ ìjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ nípasè ilé isẹ́ ètò ìlera, yóò bẹ̀rẹ̀ sìnípín àwọn àpò apa ẹ̀fọn tó lé ní milliónu márun fáwọn ilé kọ́ọ̀kan tón bẹ yíká gbogbo àwọn ìjọba ìbílẹ̀ nípinlẹ̀ ọ̀yọ́.

Igbákejì olùdarí ẹ̀ka òtò ìlera, aráàlu nílesẹ́ ètò ìlera ọ̀hún, Díkítà Olubunmi Ayinde tó sísọ lójú ọ̀rọ̀ náà nínú ìpàdé àwọn oníròyìn kan tó wáyé nílu ìbàdàn, sàlàyé pé, ìgbésẹ̀ náà ló wà níbamu pẹ̀lú àjọsepọ̀ ilé isẹ́ ètò ìlera ìjọba àpapọ̀ àtìjọba ilẹ̀ America.

Dókítà Ayinde fi kálàyé rẹ̀ pé, ọjọ́ kejìdínlógún bẹ̀ẹ̀rẹ̀ sini pín àpò apa ẹ̀fọn náà, lẹ́yìn táwọn èèyàn bá ti gbawọn iwe pélébé pélébé tíwọ́n yóò fi leto si àpò apa ẹ̀fọn ọ̀hún ni gbigba, èyí tí yóò wáyé láàrin ọgbọnjọ osùkejì sí ọjọ́ keje osù kẹjọ ọdún yíì.

Kò sài fikun pé, mímú ilégbe ẹnikọọ kan ni wọ́n yóò kó àwọn káàdi kékèké náà lọ, tó sì rọ àwọn èèyàn láti ridajú pé wọ́n gbàwọn káàdi ọ̀hún, nítorí pé, tíwọ́n kò bá tiri gbà, wọn kò ní lánfàní láti gba àpò apa ẹ̀fọn náà.

Net/Wojuade     

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *