Apákan ilé alájàméjì tí wọ́n ńkọ́ lọ́wọ́ nílu Abuja ti dàwó pẹ̀lú olùgbé kan nínú ilé náà tó jọ́lọ́hun nípè.

Ilé ọ̀hún tó dàwó lówà lẹ́yìn Cites Estate lójú ọ̀nà pápákọ̀ òfurufú ní Jabi.

Ìsẹ̀lẹ̀ náà, gẹ́gẹ́bí ọ̀gá àgbà àjọ tó ń mójútó ìsẹ̀lẹ̀ pàjáwìrì ẹkùn Abuja, Àlhájì Abbas Idris sewi, ló sẹlẹ̀ lọ́wọ́ òru.

Òkú ẹni tó bá ìsẹ̀lẹ̀ ọ̀hún rìn ni wọ́n ni wọ́n ti gbé lọsí ilé ìwòsàn ìjọba àpapaọ̀ tówà lágbègbè Jabi nílu Abuja.

Gẹ́gẹ́bí Àlhájì Idris sewí, ó ní àwọn tón gbẹnu ilé àkọ́pa tì náà ni wọ́n ti dóòla lọ sí àyè mi kole dẹ́kun lílùgbàdì ikú òjijì mi pẹ̀lú bílé náà se n ya lulẹ̀ diẹ.

Ọmọlọla Alamu/Ayọdele Ọlaọpa

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *