Yoruba

Ilẹ̀ Nàijírìa tẹ́wọ́gba awọn nkan ìsembáyé ìlú Benin padà

Orílẹ̀èèdè Nàijírìa ti tẹ́wọ́gba awọn ǹkan ìsẹ̀mbáyé ìlú Bẹnin padà látọwọ́ ilé-ẹ̀kọ́ gíga fasítì Cambridge, lẹ́yìn ọgọ́run ọdún tí wọ́n ti kó kúrò nílẹ̀yí.

Níbi ètò kan tó wáyé nílẹ̀ gẹẹsi, nílé ẹ̀kọ́ Jesus College, ló ti fa àwọn ǹkan ìsẹ̀mbáyé lọ́jọ̀ si nílẹ̀yí lọ́wọ́.

Ikọ̀ asójú ilẹ́yí, tówà níbi ètò náà, ni ọ̀jọ̀gbọ́n Abba Tijani léwájú fún.

Ọjọgbọn Tijani wá fi ìdùnnú rẹ̀ hàn pé, àwọn ohun isẹ́mbáyé náà tí wọ́n pè ní Òkukòr lósì wá nípò tó dára.

A o ránti pé ọdún 1897 ni wọ́n gbé àwọn ǹkan ìsẹ́mbáyé náà kúrò nílu Benin.

Folakemi Wojuade