Yoruba

Gómìnà ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ onímọ̀ ẹ̀rọ Seyi Makinde ti késí àwọn aráàlu, àwọn ilé isẹ́, àwọn ẹlẹ́yinjú anu, lájọlájọ àtàwọn min tọ́rọnkàn lórí síse ìkúnlọ́wọ́ fúnjọba fún ìgbáyégbádùn àwọn tókùn diẹ káàto fún nípinlẹ̀ yí.

Gómìnà pe ìpè náà lásìkò ayẹyẹ fífa ilé gbe àwọn ọkùnrin ohun ófìsì tódi títúnse ní ọgbà àtúnse àwọn mọ̀jèsín àti ti ìtọ́jú àwọn ògo wẹrẹ tówà lágbègbè ijokodo pẹ̀lú ọwọ ọrẹ ibùsùn látọ̀dọ̀ bánki kan.

Gómìnà Makinde tí àkọ̀wé àgbà ilé isẹ́ tówà  fọ́rọ̀ àwọn obìnrin ohun ọrọ àwùjọ, arábìnrin Christiana Abioye sojúfún sàlàyè pé rírísí ìgbáyégbádùn àwọn tó ku diẹ káto fún láwùjọ ni yóò fún wọn nírètí ọjọ́ ọ̀la tó dára.

Nígbà tó ń sàpèjúwe ìgbésẹ̀ bẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìwà sise anu, Gómìnà Makinde sọpé dídásí ọ̀rọ̀ àwùjọ pẹ̀lú nínawọ́ ọrẹ lójẹ́ ìwà tó da gba.

Ayodele Ọlaọpa  

Yoruba

Àjọ tó ń rí sí ìpeniye ǹkan ìlò nílẹ̀ Níajírìa SON, ti sèkìlọ̀ fáwọn iléésẹ́ tó ń pèsè irin pé kí wọ́n mójútó àwọn irin-isẹ́ tí wọ́n ńlò fún ìpèsè irin.

Olùdarí àgbà àjọ SON, ọ̀gbẹ́ni Farouk Salim tó sípayá ọ̀rọ̀ yí níbi àpéjọpọ̀ kan tó wáyé nílu Abuja sọ́ọ̀ di mímọ̀ pé àjọ náà ti se àlàkalẹ̀ ìlànà lórí irin-isẹ́ tí wọ́n gbọdọ náà tẹlẹ.

Ó tọ́ka si pé àjọ SON kojú osuwọn láti máà se atọ́nà lórí iri-isẹ́ tí wọ́n gbọdọ̀ máà lò láwọn iléèsẹ́ bíì èyí ti ń pèsè irin-tutu, iléèsẹ́ ojú omi pẹ̀lú iléèsẹ́ èròjà epo rọ̀bì àti afẹ́fẹ́ gáàsi.

Ọgbẹni Salim tún sọ́ọ̀ di mímọ̀ pé gbogbo ǹkan ti wọn fi ń se òdiwọ̀n àti àwọn irin-isẹ́ tí wọ́n ń lò níléèsẹ́ tó ń pese asọ ni wọn gbọdọ máà tọpinpin wọn, kí ohun gbogbo le máà lọ déèdé.

Babatunde Salaudeen