Yoruba

Ilé ìfowópamọ́ tón r;is;i ìdàgbàsókè ilẹ̀ adúláwọ̀, AFDB, àti àjọ tón rí sétò ìsúná ìdàgbàsókè ẹ̀ka ètò ọ̀gbìn nílẹ̀ òkèrè, IFAD, ti mú ìpínlẹ̀ Ògùn gẹ́gẹ́ bí ibití àkànse ètò ọ̀gbìn kan tíwọ́n sàgbékalẹ̀ yóò ti wáyé.

Olùdarí àjọ IFAD, nílẹ̀ yíì, ọ̀mọ̀wé Patrick Habamenshi ló sọ̀rọ̀ yíì di mímọ̀, lákokò tí ikọ̀ rẹ̀ àti ti ilé ìfowópámọ́ tón rísí ìdàgbàsókè ilẹ̀ adúláwọ̀ sàbẹ̀wò ẹnusẹ́ sí Gómìnà ìpínlẹ̀ Ògùn, ọmọba Dapọ Abiọdun lágbègbè òkè Mosan nílu Abẹokuta.

Ọmọwe Patrick sọpé àwọn ànfàní tópọ̀ ló sodo sẹ́ka ètò ọ̀gbìn èyí tó lé mú ìlọsíwájú bá, ìdí, sini yi tó fi sepàtàkì fún ìjọba láti dókoowò sẹ́ka ọ̀hún.

Nígbà tó ń báwọn ikọ̀ náà sọ̀rọ̀, Gómìnà ìpínlẹ̀ Ògùn, ọmọọba Dapọ Abiọdun sàlàyé pé, inú òun dùn gidigidi bíwọ́n se mú ìpínlẹ̀ Ògùn láàrin àwọn ìpínlẹ̀ tón bẹ lórílẹ̀dè yíì láti jànfàní látara tíwọ́n fẹ́ bgékalẹ̀ náà pẹ̀lú àtọ́kasí pé, isẹ́ àkànse ọ́hún ló wà níbamu pẹ̀lú èróngbà ìsèjọba òun lẹ́ka ètò ọrọ̀ ajẹ́.

Aminat/Wojuade

News Yoruba

Ìjọba àpapọ̀ ti setán láti gba àwọn akẹ́kọ jáde, ilé ẹ̀kọ́ gíga ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgbọ̀n níye sẹ́nu isẹ́ lẹ́ka ètò ọ̀gbìn láti sàtìlẹyìn fáwọn àgbẹ̀ yíká orílẹ̀ èdè yí.

Akọ̀wé àgbà, fún ẹgbẹ́ tón mójútó ètò ọ̀gbìn àti ìdàgbàsókè ilẹ̀, ọ̀gbẹ́ni Paul Ikonne ló sọ̀rọ̀ yí fáwọn akọ̀rìnyìn nílu Abuja pẹ̀lú àlàyé pé àwọn akẹ́kọ jáde yi ni wọn ma se ìdánilẹ́kọ fún lórí ẹ̀ka ọ̀gbìn tófimọ́ gbígbà oníruru ilẹ̀ àti sísàyẹ̀wò rẹ̀.

Oní wọ́n yo gba wọn sísẹ́ lábẹ́ ilésẹ́ tón mójútó àwọn ọ̀dọ́ àgbẹ̀ .

Ó sọ di mímọ̀ pé ìjọba àpapọ̀ ti rọ ọ̀dọ́ àgbẹ̀ tó jẹ́ ogun níye lágbára pẹ̀lú owó tó jẹ́ milliọnu lọ́nà ọgbọ̀n naira pẹ̀lú àfikún pé, bánki tón mójútó isẹ́ àgbẹ̀ ni yo pèsè owó ọ̀hún.

Fadahunsi/Afonja