Ìjọba àpapọ̀ ti setán láti gba àwọn akẹ́kọ jáde, ilé ẹ̀kọ́ gíga ẹgbẹ̀rún lọ́nà ọgbọ̀n níye sẹ́nu isẹ́ lẹ́ka ètò ọ̀gbìn láti sàtìlẹyìn fáwọn àgbẹ̀ yíká orílẹ̀ èdè yí.

Akọ̀wé àgbà, fún ẹgbẹ́ tón mójútó ètò ọ̀gbìn àti ìdàgbàsókè ilẹ̀, ọ̀gbẹ́ni Paul Ikonne ló sọ̀rọ̀ yí fáwọn akọ̀rìnyìn nílu Abuja pẹ̀lú àlàyé pé àwọn akẹ́kọ jáde yi ni wọn ma se ìdánilẹ́kọ fún lórí ẹ̀ka ọ̀gbìn tófimọ́ gbígbà oníruru ilẹ̀ àti sísàyẹ̀wò rẹ̀.

Oní wọ́n yo gba wọn sísẹ́ lábẹ́ ilésẹ́ tón mójútó àwọn ọ̀dọ́ àgbẹ̀ .

Ó sọ di mímọ̀ pé ìjọba àpapọ̀ ti rọ ọ̀dọ́ àgbẹ̀ tó jẹ́ ogun níye lágbára pẹ̀lú owó tó jẹ́ milliọnu lọ́nà ọgbọ̀n naira pẹ̀lú àfikún pé, bánki tón mójútó isẹ́ àgbẹ̀ ni yo pèsè owó ọ̀hún.

Fadahunsi/Afonja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *