Yoruba

Ilé ìgbìmọ̀ asòfin kejì ti rọ ilé-isẹ́ panápaná ìjọba àpapọ̀ látiridájú pé, wọ́n pèsè àwọn ẹ̀rọ tí yóò máà ta àwọn aráàlu lólobó tísẹ̀lẹ̀ ìjàmbà iná bá fẹ́ wáyé yíká àwọn ọjà tónbẹ lórílẹ̀dè yíì, láti dábobo ẹ̀mí àti dúkia aráàlu àti láti dènà ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbà iná lemọ́lemọ́ nílẹ̀ Nàijírìa.

ọ̀rọ̀ yíì niwọ́n fẹnikò lé lórí lẹ́yìn tí wọ́n jíròrò lórí dídènà ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná nílẹ̀ Nàijírìa, èyí tí ọ̀gbẹ́ni Henry Nwawuba gbékawájú ilé.

Ó sàlàyé pé ọ̀rọ̀ ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná ti wa ńdi lemọ́lemọ́ nílẹ̀ Nàijírìa, ìdí sinni yí tó fi sepàtàkì láti pinwọ́ rl, fi dabobo ẹ̀mí àti dúkia aráàlu, ọ̀gbẹ́ni Nwawuba kò sài fikun pé, àwọn ọ̀rọ̀ náà tó bá wa láwọn ojú táyé, yóò jẹ́ kó rọrùn fáwọn èèyàn tó bá nibi ìsẹ̀lẹ̀ náà tètè kópa rẹ̀ káwọn òsìsẹ́ panápaná tó dé.

Aminat/Wojuade   

Yoruba

Àjọ elétò ìdìbò ilẹ̀ yí, INEC, ti ní ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná tó wáyé lápá ibìkan nílé isẹ́ nà tó wà nílu Àkúrẹ́ kò ní nípa lórí ètò ìdìbò Gómìnà tí yio wáyé ní ọjọ́ kẹwa osù tó ńbọ̀ nípinll Òndó.

Alága ẹ̀ka tó wà fún ìdánilẹ̀kọ olùdìbò nínú àjọ ọ̀ún, ọ̀gbẹ́ni Festus Okoye ló sọ̀rọ̀ yí di mímọ̀ nígbàtí ó ńsọ̀rọ̀ lórí ìjàmbá iná náà.

Ọgbẹni Okoye wá ní kí àwọn ẹgbẹ́ òsèlú tó fẹ́ kópa nínú ètò ìdìbò náà máà se jk pé àjọ elétò ìdìbò yóò sán gbogbo ọ̀nà láti sàgbékalẹ̀ ẹ̀rọ tó ń sàyẹ̀wò káàdi olùdìbò mín-in, ni wọ́n bá gba tó jẹ́ pé, ètò ìdìbò ọ̀hún nìkan lówà fún ìpínlẹ̀ ọ̀hún.

Alákoso náà kò sài tọ́kasi pé, ó lé ẹgbẹ̀rún márun àwọn ẹ̀rọ ọ̀hún tó jóná sínú ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná tó wáyé, tó sì fikun pé, àjọ INEC, yóò sèwádíì fínífíní lórí ohun tó sokùnfà ìsẹ̀lẹ̀ ìjàmbá iná náà.

Abudu/Wojuade