Yoruba

Gómìnà ìpínlẹ̀ Ògùn, ọmọba Dapọ Abiọdun ti fọwọ́ ìdánilójú sọ̀yà pé òun kò ní dín owó osù àwọn òsìsẹ́ kù, pẹ̀lú ìpèníjà tón dojúkọ ètò ọrọ ajé nílẹ̀ yí.

Gómìnà Abiọdun sọ̀rọ̀ ìdánilójú yi nílu Abẹokuta lásìkò tón sínu pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹ́ òsèlú All Progressive Congress APC, nílu Abẹokuta.

Óní ìsèjọba òun, yo tẹ̀síwájú láti ma sisẹ́, tí ètò ọrọ ajé ìpínlẹ̀ náà yo fi túnbọ̀ gbópọn si, láti le se isẹ́ ìríjú tó yẹ fún àwọn arálu.

Ọmọba Abiọdun wá sèlérí pé ètò ìdìbò sípò nìjọba ìbílẹ̀ tón bọ̀ nínú osù keje, lọ́jọ́ kẹrin lé lógún yíká ìpínlẹ̀ náà, ni kòní ní kọ́ninkọ́họ kankan nu.

Sherifdeen/Afọnja

News Yoruba

Kòdín ní àwọn olùgbé ìlú Abẹokuta tó jẹ́ àdọ́ta níye tí wọ́n ti fún ní ìjìyà láti sisẹ́-ìlú fún ọjọ́ méjì lẹ́yìn tí wọ́n jẹ̀bi níwájú ilé ẹjọ́ alágbeká pàtàkì ti ìjọba ìpínlẹ̀ Ògùn gbé kalẹ̀ lórí fífi ẹsẹ̀ òfin dídènà covid 19, múlẹ̀, èyí tón pọ̀si lẹ́nu lọ́lọ́ọ́ yi.

Ìgbìmọ̀ tón fi ẹsẹ̀ òfin múlẹ̀ èyí tí alákoso fọ́rọ̀ àsà àti ìrìnàjò afẹ́ nípinlẹ̀ náà, ọ̀gbẹ́ni Oluwatoyin Taiwo lé wájú rẹ̀, sọpé àwọn arálu ni kò tẹle àwọn òfin àti ìlànà yi bó se yẹ, lómú kí wan se àgbékalẹ̀ ilé ẹjọ́ pàtàkì yi.

Ìpínlẹ̀ Ògùn ti ni àkọlé o le ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà mẹ́rin, ẹni tí wọ́n ti ní àrùn covid 19 wọ́n ti yọnda èyàn tó lé ní ẹgbẹ̀rún tárawọn ti yá mẹ́ta nígbàtí àwọn mẹ́rìndínladọta bá àrùn náà rin, láti ọdún tó kọjá tó ti bẹ́ sílẹ̀.

Oluokun/Afọnja

Yoruba

Ìjọba ìpínlẹ̀ Ògùn ti sọ pàtàkì lílo ìmọ̀ ẹ̀rọ láti fi kọ́ni láti mú kí àgbéga dé bá ẹ̀ka ètò níbamu pẹ̀lú bí wọ́n tínse láwọn orílẹ̀ èdè tó ti gòkè àgbà.

Olùdámọ́ran sí Gómìnà ìpínll Ògùn lórí ètò ẹ̀kọ iléwe alákọbẹ̀rẹ̀ àti girama Arábìnrin Ronkẹ Soyọmbọ, ló sọ̀rọ̀ yí níbi àpérò kan tó wáyé, láti sáàmì àjọyọ̀ mimọko moka, fún tọdún 2020, èyí tí wọ́n pè àkòrí rẹ̀ ní kókọ́ni nípa sísàmúlò ìmọ̀ ẹ̀rọ science lásìkò ìpèníjà ìtànkálẹ̀ àrùn covid-19 papa, isẹ́ tó wà níwájú olukọ àti ìpèníjà tó sẹ̀sẹ̀ kó súyọ.

Arábìnrin Soyọmbọ tọ́kasi pé, óti pa dandan láti róò àwọn olùkọ́ lágbára níbamu pẹ̀lú on gbogbo tí wọ́n yo nílò fún kíkọ́ akẹkọ lásìkò ìtànkálẹ̀ àrùn covid-19.

Nínú ọ̀rọ̀ ọ̀tọ̀tọ̀ àwọn onímọ̀ nípa ètò ẹ̀kọ́, ọ̀jọ̀gbọ́n Adejọkẹ Jibowo láti ilé ẹ̀kọ́ gíga versity Ọlabisi Ọnabanjọ àti ọ̀gbẹ́ni Joseph Adetọna láti àjọ tó n mójútó ìdánwò àsejáde nílé wé girama WAEC, pé àwọn tọ́rọ̀ ètò ẹ̀kọ́ kàn gbọ̀ngbọ̀n láti sàmúlò ìlànà ẹ̀kọ́ni àtìjọ àti tòde òní, kí àyípadà tó yẹ le wáyé léka ètò ẹ̀kọ́.  

Afonja