News Yoruba

Gómìnà ìpínlẹ̀ ọ̀yọ, onímọ̀ ẹ̀rọ Seyi Makinde ti sọ́ọ̀ di mímọ̀ pé ìjọba rẹ̀ fún ọdún méjì àkọ́kọ́ ti mú àlékún bá owó tí wọ́n ń pa wọlé lábẹ́nú pẹ̀lú owó tótó billionu mẹ́ẹ̀dogun naira lái se àlékún owó orí.

Gómìnà sàlàyé ọ̀rọ̀ yí níbi ètò kan tó wáyé nílu ìbàdàn lásìkò tón fèsì sí àwọn àhesọ kan nípa ìlànà ìkówójọ fún isẹ́ ìdàgbàsókè tíjọba rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti fi di àlafo ìpèsè ùnkan amáyédẹrùn àti láti se àmúgbòrò ètò ọ̀rọ̀ ajé léyi ti yóò tún lé mu kí àgbéga bá ìlànà ìpawówọlé lábẹ́nú.

Gómìnà Makinde sàlàyé wípé àkọsílẹ̀ àjọ tó ń sètò ìsirò nílẹ̀ yí se àfihàn rẹ̀ pé àlẹ́kún ìdá méjìlélógójì ló ti bá ọ̀nà ìpawówọlé lábẹ́nú nípa bí àwọn tón san owó orí se pọ síì lái se àlékún owó orí.

Gómìnà tún sèkìlọ̀ lórí titi owó òsèlú bọ́ ìpèníjà tó ń kojú ètò áàbò nípinlẹ̀ ọ́yọ̀ pẹ̀lú àlàyé wípé léyi tí wọ́n yóò fi máà se alátakò láì la ọ̀nà àbáyọ, ó yẹ kí koriwa ó kópa nínú ìgbésẹ̀ àti jẹ́ kí ètò áàbò tó péye ó wá ní ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́.

Adebisi /Salaudeen

Yoruba

Gómìnà ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́, onímọ̀ ẹ̀rọ Seyi Makinde ti kí gbogbo àwọn mùsùlùmí nípinlẹ̀ ọ̀yọ́ kú oríre ọjọ́ ìbí òjísẹ́ ńlá Muhammad.

 Nínú àtẹ̀jáde èyí tí akọ̀wé àgbà lórí ọ̀rọ̀ ìròyìn sí Gómìnà, ọ̀gbẹ́ni Taiwo Adisa fisíta, Gómìnà rọ àwọn Mùsùlùmí láti gbé ẹ̀wù ìfẹ́, àláfìa, ìfiraẹnijì wọ̀.

Gómìnà Makinde tún fi àsìkò ọdún yi láti rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sí gbogbo àwọn tọ́rọkàn láti dákun dábọ̀ gba àláfìa láye pẹ̀lú àtọ́kasí pé isẹ́ gbogbo èyà ní láti ridájú pé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ túnbọ̀ dárasi.

 Bákanà, ẹgbẹ́ àwọn Mùsùlùmí tó jẹ́ òsìsẹ́ agbóhùnsáfẹ́fẹ́ nílẹ̀ Nàijírìa, MMPN, ẹ̀ka ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ rọ àwọn asíwájú nílẹ̀ yí láti wo àwòkọ́se ìhùwàsí òjísẹ́ ńlá Muhammad nínú èyí anu síse , níní ẹ̀rí ìfẹ́, wiwanisọkan jugbogboẹlọ ọ̀kan nínú ìdáwọ́lé wọn.

 Nínú àtẹ̀jáde èyí tí alága ẹgbẹ́ ohun Àlhájì Ridwan Fasasi fis;ita nílu’ bàdàn ni ọ̀rọ̀ yi ti jẹyọ, pẹ̀lú àtọ́kasí pé, híhùwà òdodo ni gbogbogbà, ló wà lára o n tólè gbé orílẹ̀èdè yí jòkè àgbà, dọ́gba pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ tóti gòkè àgbà lágbayé.

Adebisi/Afọnja