Alákoso fétò ìlera nílẹ̀ yíì, Dokítà Osagie Ehanire, yóò se ìpàdé pọ̀ pẹ̀lú àwọn alákoso fétò ìlera láti ìpínlẹ̀ mẹ́rìndínlógójì tówà ni orílẹ̀èdè yíì lóni, gẹ́gẹ́ bí ara akitiyan láti ridájúpé, ìsedédé pínpín wáà nídi abẹ́rẹ́ àjẹsára àrùn covid-19.
Ẹwẹ ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó sọpé, òhun si ńdúró déè, ìpín tóun, pẹ̀lú àlàyé pé ìgbésẹ̀ ti jẹ́ gbígbé láti se abẹ́rẹ́ àjẹsára náà lọjọ.
Alákoso fọ́rọ̀ ìròyìn àti àtóò gbogbo, nípinlẹ̀ Èkó, ọ̀gbẹ́ni Gbenga Ọmọtọshọ sọpé, Gómìnà ìpínlẹ̀ náà, ọ̀gbẹ́ni Babajide Sanwo-olu ti sèfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ kan tí yóò sàmújó ọ̀rọ̀ abẹ́rẹ́ àjẹsára náà.
Elizabeth Idogbe