Àwọn olùgbé ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ti kan sárá síjọba lórí àsẹ tuntun nípa sísọ ètò kólẹ̀kódọ̀tí olósosù di ọlọ́sẹ̀sẹ̀.

Wọ́n gbósùbà yi lásìkò ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú akọ̀ròyìn Radio Nigeria tó tọpinpin báwọn èèyàn se tẹ̀lé àsẹ náà si.

Wọ́n tún rọ àwọn rọ àwọn aráalu pé kí wọ́n mú ìmọ́tótó àyíká wọn lọ́kunkúdùn láti fi le ja àjàbọ́ lọ́wọ́ àjàkálẹ̀ àrùn.

Ọkan lára àwọn èèyàn náà, arábìnrin Bọlanla Taiwo sàlàyé ìgbàgbọ́ rẹ̀ wí pé ìdọ̀tí ọ̀hún ẹ̀gbin àyíká ló léè sokùnfà àjàkálẹ̀ àrùn láwùjọ.

Nínú ọ̀rọ̀ tiẹ náà, onísòwò kan, ọ̀gbẹ́ni Samuel Ọlanrewaju pàrọwà síjọba pé kí wọ́n pèsè goro ìdalẹ̀sí sáàrin ìlú láti dènà dídalẹ̀ sójú àgbàrá.

Ọgbẹni Ọlarenwaju tún késí àwọn òsìsẹ́ woléwolé pé kí wọ́n máà tọpinpin ètò kólẹ̀kódọ̀tí náà láti fi ríì dájú pé àwọn èèyàn kópa tó yẹ.

Akọ́ròyìn Radio Nigeria sàkíyèsi pé àwọn òutàgà lárin ọjà ńlá bíì Mọniya, Ọjọọ, U.I, Sango, Mọkọla, Dugbẹ àtàwọn ọjà min tilẹ̀kùn isẹ́ wọn láti fi bétò ìmọ́tótó àyíká wọn.

Ọlayiwọla/Salaudeen

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *