Yoruba

Ìgbaniwọlé sáwọn ilé ìwé ibití àwọn akẹ́kọ tí ńgbénú ọgbà ilé ẹ̀kọ́ taládaní nípinlẹ̀ Ògùn ni yio sinmi lé ìpinu àwọn alásẹ ilé ìwé àti ẹgbẹ́ àwọn òbí àti olùkọ́.

Gómìnà ìpínlẹ̀ Ògùn, ọmọba Dapọ Abiọdun ló sọ̀rọ̀ yí nígbàtí ó ńkede pé àyẹ̀wò àrùn covid-19 fún àwọn akẹ́kọ nípele ẹ̀kọ́ oníwe mẹ́wa tó ńgbé inú ilé ìwé yio jẹ́ lọ̀fẹ fún gbogbo àwọn tó wà nílé ẹ̀kọ́ t’íjọba àti t’aládani n’ípelẹ̀ náà

Nígbàtí ó ńfèsì sí ìfẹ̀hònú hàn àwọn òbí àwọn akẹ́kọ náà lórí sísan ẹgbẹ̀rún lọ́nà méèdogbọ̀n naira dandan ńdadan fún àyẹ̀wò covid-19 fún àwọn akkkọ nílé ẹ̀kọ́ aládani, Gómìnà Abiọdun ni wọ́n yíò dáwó padà fún àwọn tí wọ́n bá ti sanwó tí wọ́n sì ti wọ́gilé kíkanípá láti sàyẹ̀wò àrùn covid-19 kí wọ́n tó padà sílé ìwé.

Ó tọ́ka síì pé pẹ̀lú bí wọ́n se léè sàyẹ̀wò ẹ́ẹ̀dẹgbẹ̀ta lọ́jọ́ kan níbùdó àyẹ̀wò tí ìpínlẹ̀ náà, ó ní kò léè séèse kí wọ́n se àyẹ̀wò gbogbo wọn tán kí ìdánwò oníwe mẹ́wa tó bẹ̀rẹ̀ lọ́jọ́ kẹtàdínlógún osù yí

Bolanle Adesida/Yẹmisi Dada

Education

Ogun State Governor, Prince Dapo Abiodun has announced that the COVID-19 test for all returning SS3 boarding students will be done free of charge for students in both public and private schools across the state. 

Reacting to a recent protest by parents of SS3 boarding students in private schools over the payment of 25,000 naira for the mandatory COVID-19 test, Governor Abiodun gave the assurance that students who had paid for the tests would be refunded. 

Governor Abiodun said his administration had also canceled the compulsory COVID-19 test as a requirement for returning students in exit classes and urged private school owners to rise to the responsibility of taking care of their students.

He pointed out that with the testing capacity of 500 tests per day in the state laboratories, it might not be feasible for all boarding students to get tested and get their results before commencement of examination on 17th August 2020. 

The governor pointed out that admittance of students into boarding facilities in private secondary schools would be at the discretion of the management and the Parents Teachers Association of such private schools.

While recommending that students with underlying health conditions should attend school from home daily, Governor Abiodun said face masks would be distributed to all students in both private and public schools across the state.

Bolanle Adesida