Igbákejì àarẹ orílẹ̀èdè Nàijírìa Yẹmi Ọsinbajo ti fidá àwọn ọmọ ilẹ̀ yíì tó ńtajà lórílẹ̀èdè Ghana lójú wípé ìdájọ́ òdodo yówayé lórí ohun tí wọ́n jìjàdù rẹ̀ pẹ̀lú ìjọba ilẹ̀ Ghana.

Ọjọgbọn Ọsinbajo, ẹnitó sèpàdé pọ̀ pẹ̀lú àwọn asojú ọmọ ilẹ̀ yíì tíwà ni Accra, Ghana fọwọ́ ìdánilójú ìpinu ìjọba àpapọ̀ sọ̀yà, láti dásí ọ̀rọ̀ náà bótitọ́.

Gẹ́gẹ́ bótiwípé, ìjọba yóò ridájúpé òpin débá fífọwọ́líle mú àwọn ọmọ ilẹ̀ yíì jákè-jádò àgbáyé.

Ẹjẹ́kamúwá sí ìrántí pé, ilé ìtàjà àwọn òntàjà ilẹ̀ yíì lórílẹ̀èdè Ghana lójẹ́ títìpa fọ́pọ̀ osúù, nítorí àilesan milliọnu kan dollar tíjọba orílẹ̀èdè náà bèrè fún.

Mnt/idogbe   

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *