Ètò àgbékalẹ̀ ilégbe tó jẹ́ ọ̀kan gbogi nídi fífẹsẹ̀ èróngbà ìdúrósinsin ètò ọrọ̀ ajé ilẹ̀ yíì múlẹ̀, làfojúsùn rẹ̀ jẹ́ ìgbésẹ̀ ìrọ̀rùn fáwọn èèyàn tówó tó ń wọlé fún wọn, kó tó ùnkan.

Olùrànlọ́wọ́ pàtàkì fáarẹ Muhammadu Buhari lórí ọ̀rọ̀ ìgbáyégbádù, arábìnrin Imeh Okoh tó fìdí èyí múlẹ̀ nílu Abuja, sọpé, ètò náà kò wà fáwọn olósèlú tàbí àwọn èèyàn tó rọ́wọ́ họrí, bíkòse àwọn èèyàn tígbà kudiẹ káato fún.

Kò sài fi kálàyé rẹ̀ pé, ọ̀kan lára èróngbà ìsèjọba tó wà lóde báyíì ni ìpèsè ilégbe fáràalú yíká orílẹ̀dè yíì, pẹ̀lú àtọ́kasí pé, àwọn ilégbe náà ni yóò jẹ́ ojúlówó, tí yóò sì kójú òsùwọ̀n lai fiti owó péréte tíwọ́n yóò máà gbà lórí rẹ̀ se.

Arábìnrin Okoh tún se lálàyé pé, ètò náà ló wà fáwọn tówó tón wọlé fún wọn ti ìbẹ́sílẹ̀ àrùn covid-19 ti se ìpalára fún.

Aminat/Wojuade

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *