Àwọn ọmọdé nílu ìbàdàn tíi solúùlu ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ti késíjọba láti sàgbékalẹ̀ àwọn ìlànà kan tí yóò dábobo ọjọ́ ọ̀la wọn.

Lákokò tíwọ́n ńbá ilé-isẹ́ Radio Nigeria sọ̀rọ̀ ni wọ́n pè féyíì, pẹ̀lú àlàyé pé, àwọn ọjọ́ ọ̀la ilẹ̀ Nìajírìa, torina ló fi sepàtàkì fún ìjọba àtàwọn tọ́rọkàn, láti jẹ́ olótotọ́ nídi ìgbésẹ̀ dídàbòbò ẹ̀tọ́ àwọn ọmọdé.

Diẹ lára àwọn ògo wẹrẹ ọ̀hún kò sài tún rọ ìjọba láti pèsè ètò àbò tó gbópọn yíká àwọn ilé-ìwé gbogbo tó ńbẹ nílẹ̀ yíì.

Àwọn ọmọdé ọ̀hún wá fẹ̀mí ìmóòre wọn hàn sọ́lọrun ọba lórí bóse dá ẹ̀mí wọn sí, láti tún fojú gánní àyéjọ́ ọjọ àwọn ọmọdé fún tọdún yíì.

Int/Ololade Afọnja.

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *