News Yoruba

Àwọn tó fẹ́ gba ìtọ́jú kúrò lọ́wọ́ àrùn kókóró HIV nílèwòsàn ìjọba Heart to Heart nílu ọ̀yọ́ ńfẹ́ kí àmúbgòrò débá ètò ìgbáyégbádùn èyí tí ẹ̀ka tikise tìjọba gbé kalẹ̀, láti lèjẹ́ kí wọ́n lè borí ìpèníjà ètò ọrọ ajé tó ń bá ill yí fínra.

Lára àwọn tó ní àrùn yí tó bá akọ̀ròyìn ilésẹ́ Radio Nigeria sọ̀rọ̀, sọpé pẹ̀lú bí àdínkù se débá on tí àwọn àjọ tikise tìjọba pèsè bi on tẹ́nuńjẹ , àti owó ọkọ̀ tin sàkóbá fún ọ̀pọ̀ wọn.

Nínú ọ̀rọ̀ olùdarí àjọ tikise tìjọba kan nílu ọ̀yọ́, Bishọbu àgbà Ayọ Ladigbolu sàlàyé pé, bótilẹ̀jẹ́pé lára àwọn àjọ yi ti dáwọ́ ọrẹ wọn dúró, àmọ́ àjọ tí òun léwájú rẹ̀, sin pèsè on ìdẹ̀rùn, bótilẹ̀jẹ́pé bọ́wọ́ eku ti mọ ló se fin rọrí.

Ó wá rọ gbogbo èyàn tówà lágbègbè náà láti lọ se àyẹ̀wò kòkòrò HIV, látìgbàdégbà , wípé àwọn yo sì tẹ̀síwájú nínú ni náàwọ́ ọrẹ sí wọn.

Àkọ́ọ̀sílẹ̀ fihàn pé ó lé ní ẹgbẹ̀rún mẹ́rin àwọn tóní àrùn yí tón lọ gba ìtọ́jú ní Heart to heart Clinic láti bi ọdún mẹ́rin sẹ́yìn.

Oguntọna/Afọnja

News Yoruba

Alákoso fọ́rọ̀ ìròyìn àti àsà, Àlhájì Lai Mohammed ti rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sáwọn ilẹ̀ tóti gòkè àgbà láti se àtìlẹ́yìn fún orílẹ̀èdè Nàijírìa pẹ̀lú àwọn irinsẹ́ tó yẹ láti lè wọ̀ yája pẹ̀lú ìgbésùnmọ̀mí.

Ó rawọ́ ẹ̀bẹ̀ yí lásìkò tó se àbẹ̀wò ẹkúsẹ́ ńbẹun sí Gómìnà Samuel Ortom nílèjọba tó wà ní Markurdi.

Àlhájì Muhammed sọ pé ìgbésùmọ̀mí jẹ́ ìpèníjà tó ń bá gbogbo àgbáyé fínra ìdínìyí tó fi yẹ kí àwọn orílẹ̀ èdè lágbayé se àtìlẹ́yìn fún Nàijírìa lórí o n èlò láti gbógun ti ìgbésùnmọ̀mí.

Alakoso sàpèjúwe, ìkọlù tó wáyé láipẹ yi nípinlẹ̀ Borno èyí tí wọ́n ní ikọ̀ Boko haram ló wà nídi ìkọlù náà, níbití ọ̀pọ̀ èyàn ti jẹ́ pípa gẹ́gẹ́bí èyí tókùdiẹ káto ó wá sèlérí pé ilẹ̀ yí yo tẹ̀síwájú láti ma sa gbogbo ipá rẹ̀ láti dábobo ẹ̀mí àti dúkia àwọn èyàn àwùjọ.

Jibikẹ/Afọnja