News Yoruba

Ìgbìmọ̀ Gómìnà nílẹ̀ Nàijírìa sàlàyé ọ̀rọ̀ lórí ẹ̀dùn kíkó ǹkan ìrànwọ́ pamọ́ lọ́nà àitọ́.

Àwọn Gómìnà nípinlẹ̀ mẹ́rìn dín lógún lábẹ́ àsía ìgbìmọ̀ nílẹ̀ Nàijírìa, ni wọ́n ti sọpé àwọn kokoo, àwọn ǹkan ìrọ̀rùn tó wà fún àwọn tó kudiẹ káto fún láwùjọ pamọ́ lásìkò tí fífi òpin sí ìtànkálẹ̀ àrùn covid-19 le dandan.

 Àwọn Gómìnà ló sọ̀rọ̀ yí di mímọ̀ nínú àtẹ̀jáde èyí tí olórí lẹ́ka tón mójútó ọ̀rọ̀ ìròyìn, àtọ̀rọ̀ tókan àwùjọ fún ìgbìmọ̀ náà, ọ̀gbẹ́ni Abudulrazaq Bello-Barkindo fisíta, lásìkò ti wọn ńfi ìhà wọn hàn sí báwọn tó ń se ìfẹ́húnúhàn se ń kó àwọn èròjà yi láwọn ìpínlẹ̀ kan lórílẹ̀ èdè yí.

 Ìgbìmọ̀ Gómìnà nílẹ̀ yí sọ pé kòsí ìpínlẹ̀ kankan ó, tó lọ́wọ́ nínú gbígbé èròjà ìrànwọ́ pamọ́ lọ́nà àitọ́.

 Wọn sì sọ̀rọ̀ ìdánilójú pé, gbogbo àwọn tó fún wọn ní ẹ̀bùn ìrànwọ́ àti ìrónilágbára sáàjú káwọn èyàn kan tó já ilé ìkẹ́rùsí, ló jẹ́ pé gbogbo rẹ̀ pátá làwọn ni àkọ́lẹ fun bóse tí n wọlé.

Ololade Afọnja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *