Akọ̀wé ẹgbẹ́ òsìsẹ́ ẹ̀ka típínlẹ̀ ọ̀yọ́, ọ̀gbẹ́ni Muhammed Ibrahim, sọpé àwọn ọmọ ìsọọta ti báà ọkọ̀ tótóó mọ́kànlá tójẹ́ tàjọ olómi ẹ̀rọ nípinlẹ̀ ọ̀yọ́ jẹ́.

Ẹwẹ àwọn òsìsẹ́ àjọ ọ̀hún ti gùnlé ìyansẹ́lódì, tí wọ́n si se ìwọ́de lána òde yíì pẹ̀lú ìlérí títẹ̀síwájú nínú ìwọ́de náà lówurọ̀ òní.

Nígbà tó ńbá akọ̀ròrìn wa sọ̀rọ̀, ọ̀gbẹ́ni Ibrahim sọpé àwọn ọmọ ìsọta, wáà nikanbi agoo kan òòru, nílé-epo kan lágbègbè Agọdi, tíwọ́n bá àwọn ọkọ̀ jẹ́ tíwọ́n sìtún kóò àwọn kọ́rọ́rọ́ ọkọ̀ náà lọ.

Ọgbẹni Ibrahim wá rawọ́ ẹ̀bẹ̀ sáwọn òsìsẹ́ ọ̀hún láti ni suuni, pẹ̀lú àlàyé pé wọn kòní séwẹ́lé ìyansẹ́lódì náà, àyààfi tíjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ báà wójùtú sọ́rọ̀ náà.

Fawọle/Idogbe

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *