News Yoruba

Ìjọba Àpapọ̀ Fèsì Lórí Bílẹ̀ Gẹ́ẹ̀sì Se Yọ Orúkọ Ilẹ̀ Nàijírìa Kúrò Nínú Orúkọ Àwọn Orílẹ̀èdè Téwu Àjàkálẹ̀ Wà

Ìjọba àpapọ̀ ti fìdùnú rẹ̀ hàn lórí bí ilẹ̀ gẹ́ẹ̀sì se yọ ilẹ̀yí kúrò nínú ọ̀kan lára àwọn orílẹ̀èdè téwu àjàkálẹ̀ àrùn wà nílẹ̀ àgbáyé pẹ̀lú bí wọ́n se fòpin de balù ilẹ̀yí láti máse wọ ìlú gẹ́ẹ̀si nípasẹ̀ ìbẹ́sílẹ̀ àjàkálẹ̀ àrùn Omicron tẹlẹ.

Ọga àgbà ẹ̀ka ìkànsáralu nílé isẹ́ tón rísí ìgbìkègbodò òfurufú, Dókítà James Odaudu tó sọ̀rọ̀ náà lásìkò tón fọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú àwọn oníròyìn, sọpé àwọn koti rí ìwé kankan gbà láti ilẹ̀ gẹ́ẹ̀sì lórí bí wọ́n se yọ ilẹ̀yí kúrò nínú orúkọ àwọn orílẹ̀èdè téwu àjàkálẹ̀ àrùn wa níbẹ̀.

Láti arọ òní lọ, ni àwọn alásẹ ilẹ̀ gẹ́ẹ̀sì ti kéde yíyọ ilẹ̀ Nàijírìa àtàwọn orílẹ̀èdè mẹ́wa min nílẹ̀ Afrika kúrò nínú orúkọ àwọn tí wọ́n fòfin ìrìnà dè pẹ̀lú fífáàyè gba ìwọlé wọ̀de àwọn arìnrìnajò láti wọlé náà.

Ọrọ náà lótẹ̀lé bí ilẹ̀yí se kéde pé òhun yo gbe ìgbésẹ̀ ti yóò jẹ́kí ilẹ̀ gẹ́ẹ̀sì. Ilẹ̀ Canada, àti ilẹ̀ UAE, gbẹ́sẹ̀ kurò lórí òfin tófide ilẹ̀ yí.

Fadahunsi / Ọlaọpa

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *