Ìjọba àpapọ̀ ti sọ pé kòsí on ìkọ̀kọ̀ kankan lórí àbá òfin lórí omi èyí tí ilé ìgbìmọ̀ asòfin àgbà ńgbé yẹ̀wò lọ́wọ́.

Níbi àpérò kan nílu Abuja ni alákoso fọ́rọ̀ ìròyìn àti àsà, Àlhájì Lai Mohammed àti alákoso fún ọ̀rọ̀ tóníse pẹ̀lú omi, ọ̀gbẹ́ni Suleiman Adamu, sọpé ọ̀pọ̀ àwọn tón kọminú lórí àbá òfin yi, ni wọn kò mọ on pàtó tí yo pèsè tí wọ́n sin gbọ àhesọ ọ̀rọ̀ lẹ́nu àwọn miràn.

Àwọn alákoso méjèjì sọ pé àbá òfin yi ni wọn se àgbékalẹ̀ rẹ̀ láti pèsè àwọn akọ́sẹmọ́sẹ́ ti yo ma mójútó sísàmúlò gbogbo ibi ojúsàn omi fún lílò àwọn èyàn àwùjọ.

Pẹ̀lú àfikún pé, àbá òfin yi, ki se on tuntun.

Àwọn ẹgbẹ́ nínú èyí tatirí ẹgbẹ́ òsìsẹ́ NLC, ni wọ́n ní àwọn kò faramọ́ àbá òfin yi.

kẹhinde/Afọnja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *