Yoruba

Ìjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ tọwọ́ bọ̀wé àdéhùn sísanwó osù tuntun fòsìsẹ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga

Ìjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ ti tọwọ́bọ ìwé padéhùn àfẹnukò kan lórí sísanwó osù tuntun fáwọn òsìsẹ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga tó jẹ́ tìpínlẹ̀ yíì.

Ilé isẹ́ ètò ẹ̀kọ́ ìpínlẹ̀ yíì tó wà ládugbò Agodi secretariat ìbàdàn niwọ́n ti tọwọ́ àdéhùn náà.

Níbi ètò náà, lalákoso fétò ẹ̀kọ́, ọ̀gbẹ́ni Ọlasunkanmi Ọlalẹyẹ ti sọ́ọ̀di mímọ̀ pé, àfẹnukò náà ló wà níbamu pẹ̀lú ìlànà ìsanwó osù òsìsẹ́ tíjọba àpapọ̀ gbékalẹ̀.

Nínú ọ̀rọ̀ tiẹ̀, alága àgbáríjọpọ̀ ẹgbẹ́ òsìsẹ́ láwọn ilé ẹ̀kọ́ gíga tó jẹ́ tìpínlẹ̀ ọ̀yọ́, ọ̀gbẹ́ni Sẹgun Oyewumi, sọ pé, àdéhùn náà yóò sànfàní fáwọn ọmọ ẹgbẹ́ ọ̀hún, pẹ̀lú àrọwà síjọba ìpínlẹ̀ ọ̀yọ́ pé, kò ní gbogbo àwọn ìlérí rẹ̀ se.

Adebisi/Wojuade

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *