Ìjọba àpapọ̀ ti fẹ́ sèdásílẹ̀ ibùdó ìmọ̀ ẹ̀rọ àti ọgbọ́n àtinúdá mẹ́fà sáwọn ẹkùn ibùdó mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tó wà lórílẹ̀ èdèyí.

Ìgbésẹ̀ yí jẹ́ láti sàmúlò àwọn àbọ̀ isẹ́ ìwádi láti fi pèsè àwọn ohun èlò tó léè tankàngbọ̀n lágbayé.

Alákoso fọ́rọ̀ ìmọ̀ sciensi, ìmọ̀ ẹ̀rọ àri ọgbọ́n àtinúdá, Ogbonnaya Onu, ló sọ̀rọ̀ yí lásìkò tó lọ sàbẹ̀wò sí Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano, Abdulahi Ganduje lórí ìgbésẹ̀ àti sèdásílẹ̀ ibùdó tí yio wà lẹ́kùn ìwọ̀ óòrùn àríwá ilẹ̀ yí sípinlẹ̀ Kano.

Ọgbẹni Onu bu ẹnu àtẹ̀ lu bí wọ́n kíì séè sàmúlò àwọn àbọ̀ isẹ́ ìwádi nítorípé gbogbo àwọn tọ́rọkàn ńdásẹ́ wọn se ni.

Ó wá béèrè fún jíjíròrò papọ̀ láàrin àwọn àjọ tó ńrísí ọ̀rọ̀ isẹ́ ìwádi, lájọlájọ ilé ẹ̀kọ́ gíga àti àwọn ilé ẹ̀kọ́ gbogbo níse bí wọn bá ńgùnlé isẹ́ ìwádi.

Ọlarinde/ Afonja

pub-5160901092443552

Related Posts

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *