Àarẹ Muhammadu Buhari ti gba ẹ̀bẹ̀ àarẹ orílẹ̀èdè South-Africa, Cyril Ramaphosa sí ilẹ̀ yíì, lórí ìkọlù tówáyé lórílẹ̀dè náà. Àarẹ Buhari ẹnitó sàpèjúwe ìkọlù náà gẹ́gẹ́ bí èyító burú jai, fọwọ́ ìdánilójú sọ̀yà pé, ìbásepọ̀ tódánmọ́rán yóò wáyé lọ́tun l’árin àwọn orílẹ̀èdè méjèjì. Ó mu wá Continue Reading
Yoruba
Ẹgbẹ́ àwọn tó ńpèsè ǹkan nílẹ̀ Nàijírìa MAN, sọ pé àtúntò tówáyé lẹ́ka ìgbìmọ̀ tó ńrísí ìgbaninímọ̀ràn fétò ọrọ̀-ajé EAC, látọwọ́ àarẹ Buhari jẹ́ èyí tódara gba, lákokò tó yẹ tó sì ńfìdí ìpinu àarẹ fétò ọrọ̀-ajé tó dúró re múlẹ̀. Nínú àtẹ̀jáde kan tólùdarí àgbà fẹ́gbẹ́ MAN, ọ̀gbẹ́ni Muda Yusuf fisíta ó pèfún àtúnyẹ̀wò […]Continue Reading
Àwọn iléékọ alákọbẹ̀rẹ̀ àti girama tó jẹ́ taládani àti tìjọba nípinlẹ̀ Ọyọ wọlé padà fún sáà ètò ẹ̀kọ́ tuntun lẹ́yìn ìsinmi ọlọ́sẹ̀ mẹ́fà. Àwọn akọ̀ròyìn wa tí wọ́n lọ káakiri ìlú Ìbàdàn láarọ òní, jábọ̀ pé, láti bí aago méje láarọ òní ni wọ́n ti ńríì àwọn akẹ́kọ na tí wan ń lọ sílèwé wọn. […]Continue Reading
Lọ́jọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n osù yi ni àsekágbá ìdíje Best Ogedengbe láarin àwọn ogbábọ̀ọ̀lù tọ́jọ́ orí wọn kò kọjá ọdún mẹ́ẹ́dọgbọn wáyé. Àwọn agbábọ̀ọ̀lù Adelagun Memorial Grammar School, Odinjo nílu Ìbàdàn àti Precing Footbal Academy, Ìdí-Ayùnrẹ́ ni yo gba ìdíje àsekágbá na. Ìdíje náà ló bọ́ sí ìrántí ọdún kẹwa tí Best Ogedengbe tó jẹ́ asọ́lé fún […]Continue Reading
Orólẹ̀èdè wa Nàijírìa, ilẹ̀ olóminira Niger àti orílẹ̀èdè Chad ti ńsisẹ́ lórí àkànse ètò láti fi se àtúnse ibùdó adágún odò Chad, kí ètò ìgbáyégbádùn ba lè wà fáwọn èèyàn tó wà lágbègbè adágún odò na. Ọga àgbà àjọ kan tí wọ́n ń pè ní National Agency for the great green wall, ọ̀mọ̀wé Bukar Hassan […]Continue Reading
Ọjọgbọn kan nínú ìmọ̀ sísàwárí epo rọ̀ọ̀bì àti ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ ìwakùsà, Olugbenga Ehinola ti késí ìjọba àpapọ̀ pe kó náwó sí ọ̀rọ̀ ìpèsè èròjà tó wọn ń pè ni Hydrocarbon èyí tí wọ́n lè ma lò dípò epo rọ̀ọ̀bì, tó sì jẹ́ pé inú àpáta ni wọ́n ti ń ríì. Ọjọgbọn Ehinola sọ̀rọ̀ yí nígbà […]Continue Reading
Egbe Oselu Peoples Democratic Party, PDP, ekun iwo orun gusu, ti sope awon yoo satileyin fun egbe naa lati pe ejo kotemilorun lori idajo eyi ti igbimo ton gbo awuye wuye lori ibo aare gbe kale. Oro yi je jade ninu atejade eyi ti igbakeji agbarijopo alaga egbe oselu PDP lekun naa, Omowe Eddy Olafeso […]Continue Reading
Giwa Fasiti Oye Ekiti, Ojogbon Kayode Soremekun, tise agbekale iko eleni mejila kan latise iwadi lesekese lori on to sokunfa ifehonuhan ojo isegun tokoja ati ikolu aya Gomina Ipinle Ekiti, Erelu Fayemi, ati bi awon meji se padanu emi won ninu ikolu naa. Ninu atejade eyi ti Ojogbon Soremekun fowosi nilu Oye Ekiti ni oro […]Continue Reading
Lọ́nà àti wojutu soro àwọn ọmọ ilẹ̀ Nàìjíríà tó ń gbé làwọn ilẹ̀ ókéré àti láti dènà àwọn èèyàn kúrò lọ́wọ́ bí wọ́n ṣe ń fi wọ́n sowo lairo tì, àwọn ilé isẹ igbohunsafefe gbọ́dọ̀ gunle gbígbé àwọn ìròyìn tó yẹ jáde lọ́nà àti lè jẹ́ káwọn èèyàn mọ àwọn nǹkan tó tọ́ fún wọn […]Continue Reading
Ìjọba Ìpínlẹ̀ Òndó sọ pé owoya aladota bilionu náírà tilè ìgbìmò asofin Ìpínlẹ̀ òhun fowosi lose to kọjá niwọn yóò lo fáwọn isẹ ìdàgbàsókè èyí tí Gómìnà Olúwa Rotimi Akeredolu gbékalè. Alakoso foro ìròyìn àti ila aráàlú lóye, Ogbeni Donald Ojogo lo fìdí èyí múlẹ̀ lakoko tó ń báwọn oniroyin sọ̀rọ̀ nilu Àkúré, tó sì […]Continue Reading
Ajọ ton rí soro dúkìá bẹ̀rẹ̀ sini ṣe àyẹ̀wò ikede Gómìnà Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ Níbamu àjọ ton rí soro kikede dúkìá ẹni, tí bẹ̀rẹ̀ sini ṣe àyẹ̀wò dúkìá oni bilionu mejidinlaadota náírà èyí tí Gómìnà Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, onímò ero Seyi Makinde kéde rè losu kẹfà ọdún yìí. Olùdarí àjọ náà ńipinle Ọ̀yọ́, Ogbeni Bisi Atolagbe ló […]Continue Reading
Àjọ tón mójútó isẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ nílẹ̀ yi, NBC, ti sọ pé ilésẹ́ ìgbóhùnsáfẹ́fẹ́ tó bá tàpá sófin ìlànà tó wà fun ni yo jìyà tótọ́ lábẹ́ òfin. Olùdarí àgbà fájọ NBC, Àlhájì Modibbo Kawu ló sọ̀rọ̀ yi nílu Abuja, lásìkò ìdánilẹ́kọ ẹlẹ́kẹrin irú rẹ̀, tóma ń wáyé lọ́dọdún, tí wọn pe àkòrì rẹ̀ ní “ […]Continue Reading
Gómìnà ìpínlẹ̀ Ọyọ onímọ̀ ẹ̀rọ Seyi Makinde tifọwọ́sí ìyànsípò ìgbìmọ̀ tí yio ma se kòkáárí ìjọba ìbílẹ̀ tófomọ́ àjọ ìgbòkè gbodò ọkọ̀ ní ìpínlẹ̀ Ọyọ. Nínú àtẹ̀jáde kan t;i akọ̀wé ìròyìn àgbà sí Gómìnà, ọ̀gbẹ́ni Taiwo Adisa fisíta sọpé ọ̀mọ̀wé Rẹmi Ayodele ni alága àjọ tón rísí ọ̀rọ̀ ìjọba ìbílẹ̀ tí alága ìgbìmọ̀ àjọ ìgbòkè […]Continue Reading
Awọn Gómìnà káàkiri àwọn ìpínlẹ̀ mẹ́fẹ̀ẹ̀fà lẹ́kùn ìwọ̀orùn orílẹ̀èdè yíì ti fẹ́ parí ìlànà ètò ààbò alájùmọ̀se Bí ọ̀rọ̀ ìpèníjà ètò àbò se ńdi ìràwọ̀ ọ̀sán lórílẹ́èdè yíì, bẹ́ẹ̀ náà làwọn Gómìnà káàkiri àwọn ìpínlẹ̀ mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tó wà lẹ́kùn ìwọ̀orùn orílẹ̀èdè yíì ti fẹ́ parí ìlànà gbogbo láti se ìfilọ́lẹ̀ ètò ààbò alájùmọ̀se fún àabò […]Continue Reading
Ó se pàtàkì fún ìjọba òbí àta alágbàtọ́ láti máà fi ìwà ọmọlúàbí se àtìlẹyìn fáwọn ọmọ wọn Níwọ̀nba ìgbà tó jẹ́ wípé gbogbo èèyàn ló gbà pe, ọmọdé lóni ni yóò di àgbà lọ́la, àtipé ọ̀dọ́ òní ni asíwájú lẹ́yìnwá ọ̀la, ó se pàtàkì fún ìjọba, òbí àta alágbàtọ́ láti máà fi gbogbo ǹkan […]Continue Reading
Awon olugbe arin gbugbu ilu Abeokuta nipinle Ogun ni won ti pe fun idasile awon ile igbonse igbalode ki asa a ndawotele nigbangba o le dinku lawujo awon egba. Awon olugbe naa ati awon wole wole pe ipe naa lasiko ti won so tenu won lori asa didawotele nigbangba eleyi to ti di asa laarin […]Continue Reading
Bí àwọn alákoso tuntun tí yóò lakoko iléesẹ́ ìjọba kọ̀ọ̀kan se ǹgbaradì fún ètò ìbúra wọn tí yóò wáyé lọ́jọ́rú ọ̀sẹ̀ yi, wọ́n wà níbi ètò ìdánilẹ́kọ ìtọ́nisọ́nà sáájú isẹ́ ọlọ́jọ́ méjì kan nílu Abuja. Nígbà tó ńside ìdánilẹ́kọ náà, àarẹ Muhammadu Buhari tó kí àwọn tórísáyàn sípò alákoso náà, kú oríìre bẹ́ẹ̀ ló sì […]Continue Reading
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní ọ̀rọ̀ pẹ̀lú àlàyé, èyí ló kí ààrẹ Muhammadu Buhari fójú ọ̀rọ̀ pe, àsẹ ẹ̀ dáwó gbígbé owó ilẹ̀ òkèèrè kalẹ̀ fáwọn tó ńkàn tẹn ńjẹ́ wọlé sílẹ̀ yíì, tó ún pa fún bánki àpapọ̀ orílẹ̀èdè yíì, kò se lẹ́yìn ìgbìyàjú ìjọba láti mú ìdàgbàsókè bá ẹ̀ka ètò ọ̀gbìn kí ìpèsè òunjẹ […]Continue Reading
Ẹgbẹ́ òsìsẹ́ nílẹ̀ yíì, NLC, ẹ̀ka tìpínlẹ̀ Ọyọ, ti tẹnumọ́ ìdí tó fi sepàtàkì fúnjọba ìpínlẹ̀ Ọyọ láti jígìrì sọ́rọ̀ ìpèníjà sísan owó osù tuntun fáwọn òsìsẹ́ tó kéré jùlọ nípinlẹ̀ yíì. Alága ẹgbẹ́ NLC, nípinlẹ̀ Ọyọ, ọ̀gbẹ́ni Titilọla Sodo ló fìdí ọ̀rọ̀ yíì múlẹ̀ lẹ́yìn ìpàdè tíwọ́n se pẹ̀lú Gómìnà Seyi Mikinde. Ọgbẹni Sodo […]Continue Reading
Ilé asòfin ìpínlẹ̀ Ọyọ ti fọwọ́sí àwọn àbá òfin kan láti sèdásílẹ̀ ilé-isẹ́ ọ̀rọ̀ agbára, ilé-isẹ́ olókoowò àti tídasẹ́ ajé sílẹ̀, ilé-isẹ́ tón rí sọ́rọ̀ isẹ́ òde, ohun amáyédẹrùn àti tètòrìnà, tófomọ́ ilé-isẹ́ tó ń rí sọ́rọ̀ àwọn obìnrin. Àbá òfin náà tíwọ́n fọwọ́ sí níbi ìjóko ilé tó wáyé níbamu pẹ̀lú ìpinu Gómìnà Seyi […]Continue Reading
Gẹ́gẹ́bí ara ìgbékalẹ̀ láti ró àwọn ọ̀dọ́ lágbára nípasẹ̀ ìmọ̀ ẹ̀rọ òde òní, ìjọba àpapọ̀ ti ńpiyamọ ètò láti se ìdásílẹ̀ àwọn ilé ẹ̀kọ́ nípa ìmọ̀ ẹ̀rọ mẹ́fà ọ̀tọ̀tọ̀ láwọn ibìkan nílé kọ́dún yíì tó wá sópin. Mẹ́wa irúfẹ́ àwọn ilé ẹ̀kọ́ bẹ́ẹ̀, yóò tun jẹ́ dídá sílẹ̀ si láarin ọdún mẹ́ta sí àsìkò táà […]Continue Reading
Kò ní pẹ́ mọ́ọ̀, tí ibùdó alákúta- fakuta àti ìpèsè ọ̀dà kóntà fún isẹ́ ojú ọ̀nà, tí ìpínlẹ̀ Ọyọ, tí wọ́n pè ní “Pacesetters” tó wà lójú ọ́nà Maníyà sí Ìsẹ́yìn, tó ti dakúrẹtẹ̀ lọ́wọ́-lọ́wọ́ báyi, yóò bẹ̀rẹ̀ isẹ́ padà. Gómìnà Seyi Makinde, tó eléyi di mímọ̀ lákokò àbẹ̀wò níbo ni ǹkan dé dúró níbòdó […]Continue Reading
Gẹ́gẹ́ bí àayan rẹ̀ láti mú ìdàgbàsókè bá ẹ̀ka ètò ìlera lọ́dọ̀ rẹ̀, ìjọba ìpínlẹ̀ Èkìtì ti ń pín ẹ̀rọ òpó ìbára ẹni sọ̀rọ̀ lọ́nà ìgbàlóde àgbèléwò ta mọ̀ sí Tablets àti Adroid Phones, fáwọn òsìsẹ́ alábojútó àti olùtọpinpin lábẹ́ àjọ tó ńbójútó ọ̀rọ̀ àwọn ilé ìwòsàn àti láwọn ìjọba ìbílẹ̀ gbogbo tó wà nípinlẹ̀ […]Continue Reading
Wọ́n ti kéde ọ̀gbẹ́ni Debọ Ogundoyin, gẹ́gẹ́bí adarí ilé ìgbìmọ̀ asòfin ìpínlẹ̀ Ọyọ, késan-an. Asòfin Ade Babajide tó sojú ẹkùn ìdìbò àríwá Ìbàdàn kejì ló kọ́kọ́ dábáà pé, kí yan ọ̀gbẹ́ni Ogundoyin, gẹ́gẹ́bí adarí ilé asòfin ti wọn fi lọ́ lẹ̀ lóni na, lẹ́yìn na ni ọ̀gbẹ́ni Adeola Bamidele kín-in lẹ́yìn. Bákanà ni wọn ti […]Continue Reading
Àarẹ Muhamadu Buhari ti kọ̀wé sí adelé adájọ́ àgbà lórílẹ̀èdè yi, adájọ́ Tanko Muhammad, pé ó fẹ́ yan adájọ́ márun míì síì sí iléẹjọ́ tó gaajù lórílẹ̀èdè yi. Bákana ni àarẹ Buhari ti tẹ́wọ́ gbáà ìwé ìfẹ́yìntì adájọ́Walter Onnaghen, gẹ́gẹ́bí adájọ́ àgbà orílẹ̀èdè yi. Àarẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ adájọ́ Onnoghen fún isẹ́ tó se fún orílẹ̀èdè […]Continue Reading